2 Sámúẹ́lì 2:21-27 BMY

21 Nígbà náà, Ábínérì sọ fún un pé, “Yípadà sí ọ̀tún tàbí òsì; mú ọ̀kan lára àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kí o sì bọ́ ìhámọ́ra rẹ.” Ṣùgbọ́n Ásáhélì kọ̀ láti dẹ́kun lílépa rẹ̀.

22 Ábínérì tún kìlọ̀ fún Ásáhélì, “Dẹ́kun lílépa mi! Èéṣe tí èmi yóò fi lù ọ́ bolẹ̀? Báwo ni èmi yóò ti wo arákùnrin rẹ Jóábù lójú?”

23 Ṣùgbọ́n ó sí kọ̀ láti padà, Ábínérì sì fi òdì ọ̀kọ̀ gún un lábẹ́ inú, ọ̀kọ̀ náà sì jáde ní ẹ̀yìn rẹ̀: òun sì ṣubú lulẹ̀ níbẹ́, ó sì kú ní ibi kan náà; ó sí ṣe gbogbo ènìyàn tí ó dé ibi tí Ásáhélì gbé ṣúbú si, tí ó sì kú, sì dúró jẹ́.

24 Jóábù àti Ábíṣáì sì lépa Ábínérì: òòrùn sì wọ̀, wọ́n sì dé òkè ti Ámímà tí o wà níwájú Gíà lọ́nà ijù Gíbíónì.

25 Àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì sì kó ara wọn jọ wọ́n tẹ̀lé Ábínérì, wọ́n sì wá di ẹgbẹ́ kan, wọ́n sì dúró lórí òkè kan.

26 Ábínérì sì pe Jóábù, ó sì bi í léèrè pé, “Idà yóò máa parún títí láéláé bí? Ǹjẹ́ ìwọ kòì tí ì mọ̀ pé yóò korò nikẹyìn? Ǹjẹ́ yóò ha ti pẹ́ tó kí ìwọ tó sọ fún àwọn ènìyàn náà, kí wọ́n dẹ́kun láti máa lépa arákùnrin wọn.”

27 Jóábù sì wí pé, “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, bí kò ṣe bí ìwọ ti wí, nítòótọ́ ní òwúrọ̀ ni àwọn ènìyàn náà ìbá padà lẹ́yìn arákùnrin wọn.”