2 Sámúẹ́lì 23:12-18 BMY

12 Òun sì dúró láàrin méjì ilẹ̀ náà, ó sì gbàá sílẹ̀, ó sì pa àwọn Fílístínì Olúwa sì ṣe ìgbàlà ńlá.

13 Àwọn mẹ́ta nínú ọgbọ̀n olórí sì sọkalẹ̀, wọ́n sì tọ Dáfídì wá ní àkókò ìkórè nínú ihò Ádúlámù: ọ̀wọ́ àwọn Fílístínì sì dó sí àfonífojì Réfáímù.

14 Dáfídì sì wà nínú odi, ibùdó àwọn Fílístínì sì wà ní Bẹ́tílẹ́hẹ́mù nígbà náà.

15 Dáfídì sì ń pòùngbẹ, ó wí bayìí pé, “Ta ni yóò fún mi mu nínú omí kàǹga tí ń bẹ ní Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu bodè.”

16 Àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta sì la ogún àwọn Fílístínì lọ, wọ́n sì fa omi látinú kàǹga Bẹ́tílẹ́hẹ́mù wá, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu bodè, wọ́n sì mú tọ Dáfídì wá: òun kò sì fẹ́ mu nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tú u sílẹ̀ fún Olúwa.

17 Òun sì wí pé, “Kí a má rí, Olúwa, tí èmi ó fi ṣe èyí; ṣé èyí ni ẹ̀jẹ̀ àwọn ọkùnrin tí ó lọ tí àwọn tí ẹ̀mí wọn lọ́wọ́?” Nítorí náà òun kò sì fẹ́ mú un.Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ṣe.

18 Ábíṣáì, arákùnrin Jóábù, ọmọ Sérúíà, òun náà ni pàtàkì nínú àwọn mẹ́ta. Òun ni ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè sí ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, ó sì pa wọ́n, ó sì ní orúkọ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta.