Àwọn Ọba Kinni 11:34-40 BM

34 Sibẹsibẹ ó ní òun kò ní gba gbogbo ìjọba náà kúrò lọ́wọ́ Solomoni, òun óo fi sílẹ̀ láti máa ṣe ìjọba ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, nítorí ti Dafidi, iranṣẹ òun, ẹni tí òun yàn, tí ó pa òfin òun mọ́, tí ó sì tẹ̀lé ìlànà òun.

35 Ṣugbọn òun óo gba ìjọba náà kúrò lọ́wọ́ ọmọ Solomoni, òun óo sì fún ọ ní ẹ̀yà mẹ́wàá.

36 Òun óo fi ẹ̀yà kan sílẹ̀ fún ọmọ rẹ̀, kí ọ̀kan ninu arọmọdọmọ Dafidi, iranṣẹ òun, lè máa jọba nígbà gbogbo ní Jerusalẹmu, ìlú tí òun ti yàn fún ìjọ́sìn ní orúkọ òun.

37 Ó ní ìwọ Jeroboamu ni òun óo mú, tí òun óo sì fi jọba ní Israẹli, o óo sì máa jọba lórí gbogbo agbègbè tí ó bá wù ọ́.

38 Tí o bá fetí sí gbogbo ohun tí òun pa láṣẹ fún ọ, tí o sì ń rìn ní ọ̀nà òun, tí ò ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú òun, tí o pa òfin òun mọ́ tí o sì ń mú àṣẹ òun ṣẹ, gẹ́gẹ́ bí Dafidi, iranṣẹ òun ti ṣe, ó ní òun óo wà pẹlu rẹ, arọmọdọmọ rẹ ni yóo máa jọba lẹ́yìn rẹ, òun óo fi ìdí ìjọba rẹ múlẹ̀ bí òun ti ṣe fún Dafidi; òun óo sì fi Israẹli fún ọ.

39 Ó ní òun óo jẹ arọmọdọmọ Dafidi níyà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ Solomoni, ṣugbọn kò ní jẹ́ títí ayé.”

40 Nítorí ọ̀rọ̀ yìí, Solomoni ń wá ọ̀nà láti pa Jeroboamu, ṣugbọn Jeroboamu sá lọ sọ́dọ̀ Ṣiṣaki, ọba Ijipti, níbẹ̀ ni ó sì wà títí tí Solomoni fi kú.