18 Lẹ́yìn náà, Rehoboamu ọba rán Adoniramu, tí ó jẹ́ ọ̀gá àgbà àwọn tí wọn ń kó àwọn eniyan ṣiṣẹ́ tipátipá, láti lọ bá àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Rehoboamu bá múra kíá, ó bọ́ sinu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀, ó sá lọ sí Jerusalẹmu.
19 Láti ìgbà náà ni Israẹli ti ń bá ìdílé Dafidi ṣọ̀tẹ̀ títí di òní yìí.
20 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé Jeroboamu ti pada dé láti ilẹ̀ Ijipti, wọ́n pè é sí ibi ìpàdé kan tí wọ́n ṣe, wọ́n sì fi jọba Israẹli. Kò sí ẹni tí ó tẹ̀lé ìdílé Dafidi, àfi ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo.
21 Nígbà tí Rehoboamu pada dé Jerusalẹmu, ó ṣa ọ̀kẹ́ mẹsan-an (180,000) ọmọ ogun tí wọ́n jẹ́ akikanju jùlọ láti inú ẹ̀yà Juda ati ti Bẹnjamini, láti lọ gbógun ti ilé Israẹli kí wọ́n sì gba ìjọba ìhà àríwá Israẹli pada fún un.
22 Ṣugbọn Ọlọrun sọ fún wolii Ṣemaaya,
23 pé kí ó jíṣẹ́ fún Rehoboamu, ọba Juda ati gbogbo ẹ̀yà Juda ati ti Bẹnjamini,
24 pé OLUWA ni wọn kò gbọdọ̀ gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, nítorí pé arakunrin wọn ni wọ́n, ati pé kí olukuluku pada sí ilé rẹ̀, nítorí pé ìfẹ́ òun Ọlọrun ni ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ yìí. Nítorí náà gbogbo wọ́n gba ohun tí OLUWA pa láṣẹ, wọ́n sì pada sí ilé wọn bí OLUWA ti wí.