1 Ọlọrun rán wolii Jehu, ọmọ Hanani, pé kí ó sọ fún Baaṣa ọba pé,
2 “O kò jámọ́ nǹkankan tẹ́lẹ̀, kí n tó fi ọ́ ṣe olórí àwọn ọmọ Israẹli, eniyan mi. Ṣugbọn irú ìgbésẹ̀ tí Jeroboamu gbé ni ìwọ náà gbé, ìwọ náà mú kí àwọn eniyan mi dẹ́ṣẹ̀; ẹ̀ṣẹ̀ wọn sì ti mú mi bínú gidigidi.
3 Nítorí náà, n óo pa ìwọ ati ìdílé rẹ rẹ́. Bí mo ti ṣe ìdílé Jeroboamu, bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣe ìdílé tìrẹ náà.
4 Ẹnikẹ́ni ninu ìdílé rẹ tí ó bá kú láàrin ìlú, ajá ni yóo jẹ òkú rẹ̀, èyíkéyìí ninu wọn tí ó bá sì kú sinu igbó, àwọn ẹyẹ ni yóo jẹ òkú rẹ̀.”