1 Lẹ́yìn tí Solomoni ọba ti kọ́ ilé OLUWA ati ààfin rẹ̀ tán, ati gbogbo ilé tí ó fẹ́ kọ́.
2 OLUWA tún fi ara hàn án lẹẹkeji, bí ó ti fara hàn án ní Gibeoni,
3 ó wí fún un pé, “Mo ti gbọ́ adura ati ẹ̀bẹ̀ rẹ, mo sì ti ya ilé tí o kọ́ yìí sí mímọ́. Ibẹ̀ ni wọn óo ti máa sìn mí títí lae. N óo máa mójú tó o, n óo sì máa dáàbò bò ó nígbà gbogbo.
4 Bí o bá sìn mí tọkàntọkàn pẹlu òtítọ́ inú, gẹ́gẹ́ bí Dafidi, baba rẹ, ti ṣe, bí o bá ṣe gbogbo ohun tí mo pa láṣẹ fún ọ, tí o sì pa òfin ati ìlànà mi mọ́,