55 Nígbà tí Saulu rí Dafidi tí ó ń lọ bá Goliati jà, ó bèèrè lọ́wọ́ Abineri, olórí ogun rẹ̀ pé, “Ọmọ ta ni ọmọkunrin yìí?”Abineri dá a lóhùn pé, “Kabiyesi, n kò mọ̀.”
56 Ọba pàṣẹ fún un pé kí ó wádìí ọmọ ẹni tí ọmọ náà í ṣe.
57 Nígbà tí Dafidi pada sí ibùdó lẹ́yìn tí ó ti pa Goliati, Abineri mú un lọ siwaju Saulu, pẹlu orí Goliati ní ọwọ́ rẹ̀.
58 Saulu bi í léèrè pé, “Ọmọ, ta ni baba rẹ?”Dafidi dáhùn pé, “Ọmọ Jese ni mí, iranṣẹ rẹ, tí ń gbé Bẹtilẹhẹmu.”