2 Ọba 1:1-7 BMY

1 Lẹ́yìn ikú Áhábù, Móábù sọ̀tẹ̀ sí Ísírẹ́lì.

2 Nísinsìn yìí Áhásáyà ti ṣubú láàrin fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Ṣamáríà, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Bálísébúbù, òrìṣà Ékírónì, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”

3 Ṣùgbọ́n ańgẹ́lì Olúwa wí fún Èlíjà ará Tíṣíbì pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Ṣámáríà kí o sì bèèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Ísírẹ́lì ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Bálísébúbù òrìṣà Ékírónì?’

4 Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ni èyí: ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ìbùsùn tí o dúbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’ ” Bẹ́ẹ̀ ni Èlíjà lọ.

5 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”

6 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Ísírẹ́lì ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Bálísébúbù, òrìṣà Ékírónì? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dúbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àníàní ìwọ yóò kú!” ’ ”

7 Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”