19 Àti pẹ̀lú, Júdà kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Ísírẹ́lì tí wọ́n ṣe.
20 Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì; ó sì jẹ wọ́n níyà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè tí tí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
21 Nígbà tí ó ta Ísírẹ́lì kúrò láti ìdílé Dáfídì, wọ́n sì mú Jéróbámù ọmọ Nébátì jẹ ọba wọn. Jéróbóámù sì mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yípadà kúrò ní tí tẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́sẹ̀ ńlá.
22 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì forítìí nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbámù kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn
23 Títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn Ísírẹ́lì mú wọn kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí Iṣánṣà ni Ásíríà.
24 Ọba Ásíríà mú àwọn ènìyàn láti Bábílónì, Kútà, Áfà, Hámátì àti Ṣéfáfáímù wọ́n sì dúró ní ìlú Ṣamáríà láti rọ́pò àwọn ará Ísírẹ́lì. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
25 Nígbà tí wọ́n gbé bẹ́ ẹ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, Bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárin wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.