2 Ọba 23:18-24 BMY

18 “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Ṣamáríà.

19 Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Bétélì, Jòṣíàh sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Ísírẹ́lì ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Ṣamáríà, tí ó ti mú Olúwa bínú.

20 Jòṣíáyà dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì ṣun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jérúsálẹ́mù.

21 Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé: “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”

22 Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Júdà tí ó tọ́ Ísírẹ́lì, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì àti àwọn ọba Júdà. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.

23 Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Jòṣíà, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jérúsálẹ́mù.

24 Síwájú sí, Jòsíáyà sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Júdà àti ní Jérúsálẹ́mù. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hílíkíyà àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.