2 Sámúẹ́lì 18:22-28 BMY

22 Áhímásì ọmọ Sádókù sì tún wí fún Jóábù pé, “Jọ̀wọ́, bí ó ti wù kí ó rí, èmi ó sáré tẹ Kúṣì lẹ́yìn.”Jóábù sì bi í pé, “Nítorí kín ni ìwọ ó ṣe sáré, ọmọ mi, ìwọ kò ri pé kò sí ìhìn rere kan tí ìwọ ó mú lọ.”

23 Ó sì wí pé, “Bí ó ti wù kí ó rí, èmi ó sáré.” Ó sì wí fún un pé, “Sáré!” Áhímásì sì sáré ní ọ̀nà pẹ̀tẹ́lẹ̀, ó sì sáré kọjá Kúṣì.

24 Dáfídì sì jókòó lẹ́nu odì láàrin ìlẹ̀kùn méjì: Álóre sì gòkè òrùlé bodè lórí odi, ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè, ó sì wò, wò ó, ọkùnrin kan ń sáré òun nìkan.

25 Álóre náà sì kígbe, ó sì wí fún ọba.Ọba sì wí pé, “Bí ó bá ṣe òun nìkan ni, ìhìn rere ń bẹ lẹ́nu rẹ̀.” Òun sì ń súnmọ́ tòsí.

26 Álóre náà sì rí ọkùnrin mìíràn tí ń sáré: Alóre sì kọ sí ẹni tí ń ṣọ́ bodè, ó sì wí pe, “Wò ó, ọkùnrin kan ń sáré òun nìkan.”Ọba sì wí pé, “Èyí náà pẹ̀lú ń mú ìhìn rere wá.”

27 Álóre náà sì wí pé, “Èmi wo ìsáre ẹni tí ó wà níwájú ó dàbí ìsáré Áhímásì ọmọ Sádókù.”Ọba sì wí pé, “Ènìyàn re ni, ó sì ń mú ìhìn rere wá!”

28 Áhímásì sì dé, ó sì wí fún ọba pé, “Àlàáfíà!” Ó sì wólẹ̀ fún ọba, ó dojúbolẹ̀ ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó fi àwọn ọkùnrin tí ó gbé ọwọ́ wọn sókè sí Olúwa mi ọba lé ọ lọ́wọ́.”