1 Wọ̀nyí sì ni ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dáfídì.“Dáfídì ọmọ Jésè,àní ọkùnrin tí a ti gbéga,ẹni-àmì òróró Ọlọ́run Jákọ́bù,àti olórin dídùn Ísírẹ́lì wí pé:
2 “Ẹ̀mí Olúwa sọ ọ̀rọ̀ nípa mi,ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ ní ahọ́n mi.
3 Ọlọ́run Ísírẹ́lì ni,àpáta Ísírélì sọ fún mi pé:‘Ẹnìkan ti ń ṣe alákòóso ènìyàn lódodo,tí ń ṣàkóso ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
4 Yóò sì dà bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nígbà tí oòrùn bá là,òwúrọ̀ tí kò ní ìkúukùu,nígbà tí koríko tútùbá hù wá láti ilẹ̀ lẹ́yìn òjò.’
5 “Lóòtọ́ ilé mi kò rí bẹ́ẹ̀ níwájú Ọlọ́run,ṣùgbọ́n ó ti bá mi dá májẹ̀mú àìnípẹ̀kun,tí a túnṣe nínú ohun gbogbo,tí a sì pamọ́; nítorí pé gbogbo èyí ni ìgbàlà, àti gbogbo ìfẹ́ mi,ilé mi kò lè ṣe kí ó má dágbà.
6 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọ Bélíálì yóò dàbí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n tí a ṣátì,nítorí pé a kò lè fi ọwọ́ kó wọn.
7 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí yóò tọ́ wọn yóòfi irin àti ọ̀pá ọ̀kọ̀ ṣagbára yí ara rẹ̀ ká;wọn ó Jóná lúúlú níbì kan náà.”