2 Sámúẹ́lì 23:4-10 BMY

4 Yóò sì dà bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nígbà tí oòrùn bá là,òwúrọ̀ tí kò ní ìkúukùu,nígbà tí koríko tútùbá hù wá láti ilẹ̀ lẹ́yìn òjò.’

5 “Lóòtọ́ ilé mi kò rí bẹ́ẹ̀ níwájú Ọlọ́run,ṣùgbọ́n ó ti bá mi dá májẹ̀mú àìnípẹ̀kun,tí a túnṣe nínú ohun gbogbo,tí a sì pamọ́; nítorí pé gbogbo èyí ni ìgbàlà, àti gbogbo ìfẹ́ mi,ilé mi kò lè ṣe kí ó má dágbà.

6 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọ Bélíálì yóò dàbí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n tí a ṣátì,nítorí pé a kò lè fi ọwọ́ kó wọn.

7 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí yóò tọ́ wọn yóòfi irin àti ọ̀pá ọ̀kọ̀ ṣagbára yí ara rẹ̀ ká;wọn ó Jóná lúúlú níbì kan náà.”

8 Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn ọkùnrin alágbára tí Dáfídì ní:Jósébù-básébè ti ará Takímónì ni olorí àwọn Balógun, òun sì ni akọni rẹ̀ tí ó pa ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn lẹ́ẹ̀kan náà.

9 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Élíásárì ọmọ Dódò ará Áhóhì, ọ̀kan nínú àwọn alágbára ọkùnrin mẹ́ta ti wà pẹ̀lú Dáfídì, nígbà tí wọ́n pe àwọn Fílístínì ní ìjà, àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì sì ti lọ kúrò.

10 Òun sì dìde, ó sì kọlu àwọn Fílístínì títí ọwọ́ fi kún un, ọwọ́ rẹ̀ sì lẹ̀ mọ́ idà; Olúwa sì ṣiṣẹ́ ìgbàlà ńlá lọ́jọ́ náà, àwọn ènìyàn sì padà bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ láti kó ìkógun.