Dáníẹ́lì 10 BMY

Dáníẹ́lì Rí Ìran Ọkùnrin Kan

1 Ní ọdún kẹta Sárúsì ọba Páṣíà, a fi ìran kan hàn Dáníẹ́lì (ẹni tí à ń pè ní Bélítésásárì). Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ ìran náà, ó sì ní í ṣe pẹ̀lú àsìkò ìpọ́njú ńlá, òye ọ̀rọ̀ náà wá bá a nínú ìran.

2 Ní àsìkò náà, èmi Dáníẹ́lì ṣọ̀fọ̀ fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta.

3 Èmi kì í jẹ oúnjẹ tí ó dára, èmi kò fi ẹran tàbí wáìnì kan ẹnu mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi òróró para títí ọ̀sẹ̀ mẹ́ta fi kọjá.

4 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù àkọ́kọ́, bí mo ti dúró sí etí i bèbè odò ńlá Tígírísì,

5 Mo wo òkè, mo rí ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ àlà funfun, pẹ̀lú àmùrè wúrà dáradára ni ó fi di ẹ̀gbẹ́.

6 Ara rẹ̀ dàbí báálì, ojú u rẹ̀ dàbí mọ̀nàmọ́ná, ẹyin ojú u rẹ̀ dàbí iná àtẹ̀tàn, apá àti ẹṣẹ̀ rẹ̀ dàbí ìtànná ìmọ́lẹ̀ tí o kún fún idẹ, àti ohùn rẹ̀ dàbí i ti ìjọ ènìyàn púpọ̀.

7 Èmi Dáníẹ́lì, ni ẹnìkan tí ó rí ìran náà, àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú u mi, wọn kò rí i, ṣùgbọ́n ìpayà ńlá dà bò wọ́n, wọ́n sálọ wọ́n sì fi ara pamọ́.

8 Ó sì ku èmi nìkan, tí mo rí ìran ńlá yìí, kò sì ku ohun kankan fún mi, ojú u mi sì rẹ̀wẹ̀sì gidigidi, n kò sì ní agbára mọ́.

9 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ó ń sọ̀rọ̀, bí mo ṣe tẹ́tí sílẹ̀ síi, mo ṣùn lọ fọnfọn, ní ìdojúbolẹ̀.

10 Ọwọ́ kan kàn mí, ó gbé mi dìde ní ìwárìrì lórí ọwọ́ àti eékún mi.

11 Ó sọ pé, “Dáníẹ́lì ẹni tí a yànfẹ́ gidigidi gba ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ yìí yẹ̀wò dáadáa, kí o sì dìde, nítorí tí a rán mi sí ọ.” Bí ó ṣe sọ èyí fún mi, mo dìde ní ìwárìrì.

12 Nígbà náà ni ó tẹ̀ṣíwájú, pé, “Má ṣe bẹ̀rù Dáníẹ́lì. Láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fi ọkàn rẹ sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run rẹ, a gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ, mo sì wá nítorí ọ̀rọ̀ náà.

13 Ṣùgbọ́n ọmọ aládé ìjọba Páṣíà dá mi dúró fún ọjọ́mọ́kànlélógún. Nígbà náà ni Máíkẹ́lì, ọ̀kan lára ìjòyè àwọn ọmọ aládé, wá láti ràn mi lọ́wọ́, nítorí a dá mi dúró níbẹ̀ pẹ̀lú ọba Páṣíà.

14 Ní ìsinsinyí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”

15 Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́.

16 Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, Olúwa mi, n kò sì ní okun.

17 Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, Olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”

18 Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.

19 Ó sì wí pé, “Má se bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin tí a yàn fẹ́ gidigidi.” Bí ó ti sọ̀rọ̀ fún mi, ara à mí sì le, mo sọ pé, “Má a wí Olúwa mi, níwọ̀n ìgbà tí o ti fún mi ní agbára.”

20 Nígbà náà, ni ó wí pé, “Sé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ aládé Páṣíà jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ aládé Gíríkì yóò wá;

21 ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Máíkẹ́lì, ọmọ aládé e yín.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12