1 “Kọ orin ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ aládé Ísírẹ́lì
2 wí pé:“ ‘Èwo nínú abo kìnnìnu ni ìyá rẹ̀ ní àárin àwọn kìnnìún yóòkù?Ó sùn ní àárin àwọn ọ̀dọ́ kìnnìún ó sì ń tọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
3 Ó sì tọ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ dàgbà, ó sì di kìnnìún tó ní agbára,ó kọ́ ọ láti sọdẹ, ó sì ń pa àwọn ènìyàn jẹ.
4 Àwọn orílẹ̀ èdè gbọ́ nípa rẹ̀,wọ́n sì fi ẹ̀wọ̀n mú un nínú ààfin wọn.Wọn fi ẹ̀wọ̀n mu nu lọ sí ilẹ̀ Éjíbítì.