17 Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé:“ ‘Báwo ni a se pa ọ́ run, ìwọ ìlú olókìkíìwọ tí àwọn èrò okun ti gbé inú rẹ̀!Ìwọ jẹ alágbára lórí okun gbogboòun àti àwọn olùgbé inú rẹ̀;ìwọ gbé ẹ̀rù rẹlórí gbogbo olùgbé ibẹ̀.
18 Nisin yìí erékùṣù wárìrìní ọjọ́ ìṣubú rẹ;erékùṣù tí ó wà nínú òkunni ẹ̀rù bà torí ìṣubú rẹ.’
19 “Èyí yìí ní Olúwa Ọlọ́run wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
20 nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀ kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ ibi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀ kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
21 Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì sí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, ṣíbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Ọlọ́run wí.”