29 Éfúráímù náà kò lé àwọn ará Kénánì tí ó ń gbé Géṣérì jáde, ṣùgbọ́n àwọn ará Kénánì sì ń gbé láàrin àwọn ẹ̀yà Éfúráímù.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹ̀yà Ṣébúlúnì náà kò lé àwọn ará Kítírónì tàbí àwọn ará Nẹ́hálólì ṣùgbọ́n wọ́n sọ wọ́n di ẹrú. Wọ́n sì ń sin àwọn ará Ṣébúlúnì.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Áṣérì kò lé àwọn tí ń gbé ní Ákò àti Áhálábì àti Ákísíbì àti Hélíbáhà àti Háfékì àti Réhóbù.
32 Ṣùgbọ́n nítorí àwọn Áṣérì ń gbé láàrin àwọn ará Kénánì tí wọ́n ni ilẹ̀ náà.
33 Àwọn ẹ̀yà Náfítalì pẹ̀lú kò lé àwọn ará Bétì-Ṣémésì àti Bẹti-Ánátì jáde; ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Náfítanì náà ń gbé àárin àwọn ará Kénánì tí ó ti ní ilẹ̀ náà rí, ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbé Bẹti-Ṣéméṣì àti Bẹti-Ánátì ń sìn ìsìn tipátipá.
34 Àwọn ará Ámórì fi agbára dá àwọn ẹ̀yà Dánì dúró sí àwọn ìlú orí òkè, wọn kò sì jẹ́ kí wọn sọ̀kalẹ̀ wá sí pẹ̀tẹ́lẹ̀.
35 Àwọn ará Ámórì ti pinnu láti dúró lórí òkè Hérésì àti òkè Áíjálónì àti ti Ṣáíbímù, ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yà Jósẹ́fù di alágbára wọ́n borí Ámórì wọ́n sì mú wọn sìn.