32 Ṣùgbọ́n nítorí àwọn Áṣérì ń gbé láàrin àwọn ará Kénánì tí wọ́n ni ilẹ̀ náà.
33 Àwọn ẹ̀yà Náfítalì pẹ̀lú kò lé àwọn ará Bétì-Ṣémésì àti Bẹti-Ánátì jáde; ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Náfítanì náà ń gbé àárin àwọn ará Kénánì tí ó ti ní ilẹ̀ náà rí, ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbé Bẹti-Ṣéméṣì àti Bẹti-Ánátì ń sìn ìsìn tipátipá.
34 Àwọn ará Ámórì fi agbára dá àwọn ẹ̀yà Dánì dúró sí àwọn ìlú orí òkè, wọn kò sì jẹ́ kí wọn sọ̀kalẹ̀ wá sí pẹ̀tẹ́lẹ̀.
35 Àwọn ará Ámórì ti pinnu láti dúró lórí òkè Hérésì àti òkè Áíjálónì àti ti Ṣáíbímù, ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yà Jósẹ́fù di alágbára wọ́n borí Ámórì wọ́n sì mú wọn sìn.
36 Ààlà àwọn ará Ámórì sì bẹ̀rẹ̀ láti ìgòkè Ákírábímù kọjá lọ sí Ṣélà àti síwájú sí i.