17 Mánóà sì béèrè lọ́wọ́ ańgẹ́lì Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
18 Ṣùgbọ́n ańgẹ́lì Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè ọrúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
19 Lẹ́yìn náà ni Mánóà mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rúbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Mánóà àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
20 Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, ańgẹ́lì Olúwa gòkè re ọ̀run láàárin ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Mánóà àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojú bolẹ̀.
21 Nígbà tí ańgẹ́lì Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Mánóà àti aya rẹ̀ mọ́, Mánóà wá mọ̀ pé ańgẹ́lì Olúwa ni.
22 Mánóà sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
23 Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ọrẹ ṣísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”