14 Àwọn ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gílíádì. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Bẹ́ńjámínì run?”
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Ísírẹ́lì má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Ísírẹ́lì ti ṣe ìbúra yìí pé: ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì.’ ”
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsí i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣílò ní ìhà àríwá Bẹ́tẹ́lì àti ìhà ìlà oòrùn òpópó náà tí ó gba Bẹ́tẹ́lì kọjá sí Ṣékémù, àti sí ìhà gúṣù Lébónà.”
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Bẹ́ńjámínì pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà