Onídájọ́ 21:4-10 BMY

4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rúbọ ọrẹ ẹbọ sísun àti ọrẹ ìrẹ́pọ̀ (ìbáṣepọ̀, àlàáfíà).

5 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Ísírẹ́lì ni ó kọ̀ láti péjọ ṣíwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mísípà pípa ni àwọn yóò pa á.

6 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Ísírẹ́lì lónìí.”

7 Báwo ni a ó ò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.

8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “È wo ni nínú ẹ̀yà Ísírẹ́lì ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mísípà?” Wọ́n ríì pé kò sí ẹnìkankan tí ó wa láti Jabesi-Gílíádì tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.

9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkan kan láti inú àwọn ará Jabesi-Gílíádì tí ó wà níbẹ̀.

10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gílíádì wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.