17 Gílíádì jókòó ní òkè odò Jọ́dánì.Èéṣe tí Dánì fi jókòó nínú ọkọ̀ ojú omi?Ásérì jòkòó ní etí bèbè òkun,ó sì n gbé èbúté rẹ̀.
18 Àwọn ènìyàn Ṣébúlúnì fi ẹ̀mí wọn wéwu ikú;bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn Náfítalì ní ibi gíga pápá.
19 “Àwọn ọba wá, wọ́n sì jà;àwọn ọba Kénánì jàní Tánákì ní etí odo Mégídò,ṣùgbọ́n wọn kò sì gba èrè owó.
20 Àwọn ìràwọ̀ já láti ojú ọ̀run wáláti ibùjókòó wọn ni wọ́n ti bá Ṣísérà jà.
21 Odò Kísónì agbá wọn lọ,odò àtijọ́ náà, odò Kíṣónì.Má a yan lọ ìwọ ọkàn mi, jẹ́ alágbára pẹ̀lú!
22 Nígbà náà ni pátakò ẹṣẹ̀ ẹsin ki ilẹ̀,nítorí eré sísá, eré sísá àwọn alágbára wọn.
23 ‘Ẹ fi Mérósì,’ bú ni ańgẹ́lì Olúwa wí.‘Ẹ fi àwọn ènìyàn inú rẹ̀ gégùn ún kíkorò,nítorí wọn kò wá sí ìrànlọ́wọ́ OLÚWÁ,láti dojúkọ àwọn alágbára.’