Róòmù 11:3-9 BMY

3 “Olúwa, wọ́n ti pa àwọn wòlíì rẹ, wọn sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀; èmi nìkan soso ni ó sì kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi.”

4 Ṣùgbọ́n ìdáhùn wo ni Ọlọ́run fi fún un? “Mo ti paẹ̀ẹ́dẹ́gbàrin ènìyàn mọ́ sílẹ̀ fún ara mi, àwọn tí kò tẹ eékún ba fún Báálì.”

5 ẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni li àkókò ìsinsin yìí pẹ̀lú, apákan wà nípa ìyànfẹ́ ti ore-ọ̀fẹ́.

6 í ó bá sì ṣe pé nípa ti ore-ọ̀fẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti iṣẹ́ mọ́; àyàmọ̀bí ore-ọ̀fẹ́ kì í ṣe ore-ọ̀fẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe pe nípa ti iṣẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti ore-ọ̀fẹ́ mọ́; àyàmọ̀bí iṣẹ́ kì í ṣe iṣẹ́ mọ́.

7 Kí ha ni? Ohun tí Isírẹ́lì ń wá kiri, òun náà ni kò rí; ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìyànfẹ́ ti rí i, a sì ṣé àyà àwọn ìyókù le.

8 Èyí ni ìwé Mímọ́ ń wí nígbà tí ó sọ pé:“Ọlọ́run ti fi oorun kùn wọ́n,ó sì dí ojú àti etí wọn,wọn kò sì le ní ìmọ̀ Kírísítì nígbà tí a bá ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ síwọn.Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ó sì rí títí di ọjọ́ òní.”

9 Ohun kan náà yìí ni Dáfídì ọba sọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé:“Kí oúnjẹ àti àwọn nǹkan mèremère wọn tàn wọ́n,láti rò pé wọ́n rí ojú rere Ọlọ́run.Jẹ́ kí àwọn nǹkan wọ̀nyí padà dojú ìjà kọ wọ́n,kí a bá à lè fi òtítọ́ wó wọn túútúú.