Àwọn Ọba Kinni 12:15-21 BM

15 Nítorí náà, ọba kò gbọ́ ti àwọn eniyan náà, nítorí pé OLUWA alára ni ó fẹ́ kí ọ̀rọ̀ yìí rí bẹ́ẹ̀, kí ọ̀rọ̀ OLUWA lè ṣẹ, tí ó bá Jeroboamu ọmọ Nebati sọ, láti ẹnu wolii Ahija ará Ṣilo.

16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé, ọba kò gbọ́ tiwọn, wọ́n dá a lóhùn pé,“Kí ló kàn wá pẹlu ìdílé Dafidi?Kí ló dà wá pọ̀ pẹlu ọmọ Jese?Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ pada sílé yín,kí Dafidi máa bojútó ilé rẹ̀!”

17 Gbogbo Israẹli bá pada sílé wọn; ṣugbọn Rehoboamu ń jọba lórí àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wà ní ilẹ̀ Juda.

18 Lẹ́yìn náà, Rehoboamu ọba rán Adoniramu, tí ó jẹ́ ọ̀gá àgbà àwọn tí wọn ń kó àwọn eniyan ṣiṣẹ́ tipátipá, láti lọ bá àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Rehoboamu bá múra kíá, ó bọ́ sinu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀, ó sá lọ sí Jerusalẹmu.

19 Láti ìgbà náà ni Israẹli ti ń bá ìdílé Dafidi ṣọ̀tẹ̀ títí di òní yìí.

20 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé Jeroboamu ti pada dé láti ilẹ̀ Ijipti, wọ́n pè é sí ibi ìpàdé kan tí wọ́n ṣe, wọ́n sì fi jọba Israẹli. Kò sí ẹni tí ó tẹ̀lé ìdílé Dafidi, àfi ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo.

21 Nígbà tí Rehoboamu pada dé Jerusalẹmu, ó ṣa ọ̀kẹ́ mẹsan-an (180,000) ọmọ ogun tí wọ́n jẹ́ akikanju jùlọ láti inú ẹ̀yà Juda ati ti Bẹnjamini, láti lọ gbógun ti ilé Israẹli kí wọ́n sì gba ìjọba ìhà àríwá Israẹli pada fún un.