14 Ahinadabu, ọmọ Ido ni alákòóso agbègbè Mahanaimu.
15 Ahimaasi, (ọkọ Basemati, ọ̀kan ninu àwọn ọmọ Solomoni), ni alákòóso Nafutali.
16 Baana, ọmọ Huṣai, ni alákòóso agbègbè Aṣeri, ati Bealoti.
17 Jehoṣafati, ọmọ Parua, ni alákòóso agbègbè Isakari.
18 Ṣimei, ọmọ Ela, ni alákòóso agbègbè Bẹnjamini.
19 Geberi, ọmọ Uri, ni alákòóso agbègbè Gileadi, níbi tí Sihoni ọba àwọn ará Amori ati Ogu ọba Baṣani ti jọba tẹ́lẹ̀ rí.Lẹ́yìn àwọn alákòóso mejeejila wọnyi, alákòóso àgbà kan tún wà fún gbogbo ilẹ̀ Juda.
20 Àwọn ọmọ Juda ati àwọn ọmọ Israẹli pọ̀ bíi yanrìn inú òkun, wọ́n ń rí jẹ, wọ́n ń rí mu, wọ́n sì láyọ̀.