1 Nígbà tí àgbà dé sí Samuẹli, ó fi àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe adájọ́ ní ilẹ̀ Israẹli.
2 Joẹli ni orúkọ àkọ́bí, èyí àbúrò sì ń jẹ́ Abija. Beeriṣeba ni wọ́n ti ń ṣe adájọ́.
3 Ṣugbọn wọn kò tẹ̀lé àpẹẹrẹ rere baba wọn. Wọ́n nífẹ̀ẹ́ owó, wọ́n ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì ń dájọ́ èké.
4 Gbogbo àwọn àgbààgbà Israẹli bá kó ara wọn jọ, wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli ní Rama;
5 wọ́n wí fún un pé, “Wò ó, àgbà ti dé sí ọ, àwọn ọmọ rẹ kò sì tẹ̀lé àpẹẹrẹ rere rẹ. Yan ẹnìkan, gẹ́gẹ́ bí ọba fún wa, tí yóo máa ṣe alákòóso wa bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù.”