2 Sámúẹ́lì 9:4-10 BMY

4 Ọba sì wí fún un pé, “Níbo ni ó gbé wà?”Síbà sì wí fún ọba pé, “Wò ó, òun wà ní ilé Mákírì, ọmọ Ámíélì, ní Lódébárì.”

5 Dáfídì ọba sì ránṣẹ́, ó sì mú un láti ilé Mákírì ọmọ Ámíélì láti Lódébárì wá.

6 Méfibóṣétì ọmọ Jónátaanì ọmọ Ṣọ́ọ̀lù sì tọ Dáfídì wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì bú ọlá fún un.Dáfídì sì wí pé, “Méfibóṣétì!”Òun sì dáhún wí pé, “Wò ó, ìránṣẹ́ rẹ!”

7 Dáfídì sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù: nítorí pé nítòótọ́ èmi ó ṣe oore fún ọ nítorí Jónátanì baba rẹ, èmi ó sì tún fi gbogbo ilé Ṣọ́ọ̀lù baba rẹ fún ọ: ìwọ ó sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.”

8 Òun sì tẹríba, ó sì wí pé, “Kí ni ìránṣẹ́ rẹ jásí, tí ìwọ ó fi máa wo òkú ajá bí èmi.”

9 Ọba sì pe Síbà ìránṣẹ́ Ṣọ́ọ̀lù, ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Ṣọ́ọ̀lù, àti gbogbo èyí tí í ṣe ti ìdílé rẹ̀ ni èmi fi fún ọmọ olúwa rẹ.

10 Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni yóò sì máa ró ilé náà fún un, ìwọ ni yóò sì máa mú ìkóre wá, ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa rí òunjẹ jẹ: ṣùgbọ́n Méfibóṣétì ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.” (Ṣíbà sì ní ọmọ mẹ́ẹ̀dógún àti ogún ìránṣẹ́kùnrin.)