1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mósè sọ fún gbogbo Ísírẹ́lì ní ihà ìlà oòrùn Jọ́dánì, aginjù: ní òdì kejì Súfì, ní àárin Páránì àti Tófẹ́lì, Lábánì, Hásérótì àti Dísáhábì.
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Hórébù dé Kadesi-Báníyà, bí a bá gba ọ̀nà òkè Ṣéírì.)
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní osù kọ́kànlá, Mósè sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run pa láṣẹ nípa àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fún wọn.
4 Èyí sẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Síhónì ọba àwọn Ámórì, tí ó jọba ní Hésíbónì, àti Ógù ọba Básánì ni ó ṣẹ́gun ní Édírénì, ẹni tí ó jọba ní Ásítarótù.
5 Ní ìhà ìlà oòrùn Jọ́dánì tí ó wà nínú ilẹ̀ Móábù ni Mósè ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣàlàyé àwọn òfin wọ̀nyí wí pé: