18 Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èṣo ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
19 Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
20 Olúwa yóò rán ègún sóríì rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
21 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-àrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
22 Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú àrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìján ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti imúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
23 Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
24 Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eekuru ẹ̀tù ìbọn yóò sì wá sílẹ̀ láti ojú ọ̀run títí tí yóò fi pa ọ́ run.