27 Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ aṣẹ́wó tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Éjíbítì. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú aáyun, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Éjíbítì mọ.
28 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó korìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti sí kúrò.
29 Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ aṣẹ́wó rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti ìdàrúdàpọ̀ rẹ
30 ni ó mú èyí wá sórí rẹ, nítorí tí ìwọ ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si orílẹ̀ èdè, o sì fi àwọn òrìṣà rẹ́ ara rẹ jẹ.
31 Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn; Èmi yóò sì fi aago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
32 “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè:“Ìwọ yóò mu nínú aago ẹ̀gbọ́n rẹ,aago tí ó tóbi tí ó sì jinnú:yóò mú ìfisẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá,nítorí tí aago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́,aago ìparun àti ìsọdahoroaago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaríà.