Ísíkẹ́lì 40:32-38 BMY

32 Lẹ́yìn náà, ó mú mi lọ sí àgbàlá tí inú ni ìhà ilà òòrùn, ó sì wọn ẹnu ọ̀nà; ó ní ìwọ̀n kan náà pẹ̀lú àwọn tí ó kù.

33 Àwọn yàrá kéékèèkéé rẹ̀, ìgbéró ògiri rẹ̀ àti àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà rẹ̀ ní ìwọ̀n kan náà pẹ̀lú àwọn tí ó kù. Ẹnu ọ̀nà náà àti àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà ni ihò yí po. Ó jẹ́ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́ ni fífẹ̀.

34 Àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà rẹ̀ dojúkọ àgbàlá tí ìta; àwọn igi ọ̀pẹ ṣe ọ̀sọ́ sí àtẹ́rígbà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì, àtẹ̀gùn mẹ́jọ sì lọ sókè rẹ̀.

35 Gẹ́gẹ́ bí àwọn yàrá kéékèèkéé rẹ̀ ṣe rí. Àwọn ìgbéró ògiri rẹ̀ àti àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà, ó sì ní àwọn ihò yí i po. O jẹ́ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀dọgbọ̀n ní fífẹ̀.

36 Àwọn yàrá ẹ̀sọ́ rẹ̀ àwọn òpó rẹ̀ àti ìloro rẹ̀, àti fèrèsé rẹ̀ yíká: gígùn rẹ̀ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́, àti ìbú rẹ̀ ìgbọ̀nwọ́ mẹẹdọ́gbọ̀n.

37 Àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà rẹ̀ dojúkọ àgbàlá ìta; àwọn igi ọ̀pẹ ṣe ọ̀sọ́ sí àwọn àtẹ́rígbà rẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ méjèèjì, àtẹ̀gùn mẹ́jọ ní ó so mọ́ ọn lókè.

38 Yàrá kan pẹ̀lú ilẹ̀kùn wà ní ẹ̀gbẹ́ àtẹ̀wọ̀ ẹnu ọ̀nà ní ọ̀kọ́ọ́kan ẹnu ọ̀nà inú, níbi tí wọn tí ń fọ àwọn ẹbọ sísun.