1 Olúwa bá Mósè sọ̀rọ̀ ní ihà Ṣínáì nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì, ó wí pé:
2 “Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Ísírẹ́lì nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
3 Ìwọ àti Árónì ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
4 Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan tí ó jẹ́ olórí ìdílé rẹ̀ láti ràn yín lọ́wọ́.
5 Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí:Láti ọ̀dọ̀ Rúbẹ́nì, Élísúrì ọmọ Ṣédéúrì;
6 Láti ọ̀dọ̀ Símónì, Ṣélúmíélì ọmọ Ṣúrísáddáì;
7 Láti ọ̀dọ̀ Júdà, Násónì ọmọ Ámínádàbù;