7 Mánà náà dàbí èso koriáńdérì, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
8 Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le ṣè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
9 Nígbà tí ìrì bá ṣẹ̀ sí ibùdó lórí ni mánà náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
10 Mósè sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sunkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálukú ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mósè sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
11 Mósè sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá iráńṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
12 Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn bàbá ńlá wọn.
13 Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sunkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’