11 Olúwa ni ìwọ àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ takò. Ta a ni Árónì jẹ́ tí ẹ̀yin ó fi kùn sí i?”
12 Mósè sì ránṣẹ́ sí Dátanì àti Ábírámù àwọn ọmọ Élíábù. Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé “Àwa kò ní í wá!
13 Kò ha tó gẹ́ ẹ́ pé o ti mú wa jáde láti ilẹ̀ tí ń ṣàn fún wàrà àti oyin láti pa wá sínú ihà yìí? O tún wá fẹ́ sọ ara rẹ di Olúwa lé wa lórí bí?
14 Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ ìwọ kò sì tí ì mú wa dé ilẹ̀ tó ń ṣàn fún wàrà àti oyin, bẹ́ẹ̀ ni o kò sì pín ilẹ̀ ìní wa fún wa. Ìwọ ha fẹ́ sọ wá di ẹrú bí? Rárá o, àwa kò ní wá!”
15 Nígbà náà ni Mósè bínú gidigidi, ó sì sọ fún Olúwa pé, “Má ṣe gba ọrẹ wọn, èmi kò gba kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ lọ́wọ́ wọn, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì pa ẹnikẹ́ni nínú wọn lára!”
16 Mósè sọ fún Kórà pé, “Ìwọ àti ọmọ lẹ́yìn rẹ gbọdọ̀ fara hàn níwájú Olúwa lọ́la—gbogbo yín, ìwọ, àwọn ọmọ lẹ́yìn rẹ àti Árónì.
17 Kí ẹnì kọ̀ọ̀kan yín mú àwo tùràrí, kí ó sì fi tùràrí sínú rẹ̀, kí gbogbo rẹ̀ jẹ́ àádọ́tàlénígba àwo tùràrí (250) kí ẹ sì ko wá ṣíwájú Olúwa. Ìwọ àti Árónì yóò mú àwo tùràrí wá pẹ̀lú.”