6 Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró sí ẹ̀gbẹ́ ẹbọ rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Móábù.
7 Nígbà náà ni Bálámù sọ ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ jáde wí pé:“Bálákì mú mi láti Árámù wá,ọba Móábù láti òkè ìlà oòrùn wáÓ wí pé, ‘Wá fi Jákọ́bù bú fún mi;wá, kí o sì jẹ́rì i sí Ísírẹ́lì.’
8 Báwo ní èmi ó ṣe fi búàwọn tí Ọlọ́run kò fi bú?Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wíàwọn tí Olúwa kò bá wí?
9 Láti ṣónṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn,láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n.Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀ èdè.
10 Ta ni ó lè ka eruku Jákọ́bùtàbí ka ìdámẹ́rin Ísírẹ́lì?Jẹ́ kí èmi kú ikú olóòtọ́,kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dàbí ti wọn!”
11 Bálákì sọ fún Bálámù pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀ta mi bú, Ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan Ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
12 Ó sì dáhùn wí pé, “Sé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”