19 Olórí yóò jáde láti Jákọ́bùyóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
20 Nígbà náà ni Bálámù rí Ámálékì ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:“Ámálékì ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀ èdè,ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
21 Nígbà náà ní ó rí ará Kénitì ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:“Ibùgbé rẹ ní ààbò,ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
22 ṣíbẹ̀ ẹ̀yin ará Kenítì ni yóò di píparunnígbà tí Áṣúrì bá mú yín ní ìgbékùn.”
23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀:“Áì, ta ni ó lè yè nigbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
24 Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdó kọ̀ Kítímù;wọn yóò ṣẹ́gun Áṣù àti Ébérì,ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
25 Nígbà náà ni Bálámù dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Bálákì sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.