2 Nígbà tí Bálámù wo ìta ó sì rí Ísírẹ́lì tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
3 ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀:“Ó wí pé Bálámù ọmọ Béórì,òwe ẹni tí ojú rẹ̀ mọ́lẹ̀,
4 Òwe ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì là:
5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jákọ́bù,àti ibùgbé rẹ, ìwọ Ísírẹ́lì!
6 “Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde,gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá,gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn,gẹ́gẹ́ bí igi òpépé tí ó wà lẹ́bá odò.
7 Omi yóò sàn láti inú garawa:èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.“Ọba wọn yóò ga ju Ágágì lọ;ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Éjíbítì wá;wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.Wọ́n jẹ orílẹ̀ èdè run,wọ́n fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;wọ́n fi idà wọn gún wọn.