4 Òwe ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì là:
5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jákọ́bù,àti ibùgbé rẹ, ìwọ Ísírẹ́lì!
6 “Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde,gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá,gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn,gẹ́gẹ́ bí igi òpépé tí ó wà lẹ́bá odò.
7 Omi yóò sàn láti inú garawa:èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.“Ọba wọn yóò ga ju Ágágì lọ;ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Éjíbítì wá;wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.Wọ́n jẹ orílẹ̀ èdè run,wọ́n fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;wọ́n fi idà wọn gún wọn.
9 Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún,bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn?“Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ,kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
10 Nígbà náà ni ìbínú Bálákì sì dé sí Bálámù. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀ta mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.