5 Olúwa sọ fún Mósè pé,
6 “Kó ẹ̀yà Léfì wá, kí o sì fà wọ́n fún Árónì àlùfáà láti máa ràn-án lọ́wọ́.
7 Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní Àgọ́ Ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.
8 Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú Àgọ́ Ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.
9 Fi ẹ̀yà Léfì jìn Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Árónì nínú gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.
10 Kí o sì yan Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; ẹnikẹ́ni tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”
11 Olúwa tún sọ fún Mósè pé,