22 Olúwa sọ fún Mósè pé,
23 “Sọ fún Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Báyìí ni kí ẹ ṣe máa súre fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Ẹ sọ fún wọn pé:
24 “ ‘ “Kí Olúwa bùkún un yínKí ó sì pa yín mọ́.
25 Kí Olúwa kí o mú ojú rẹ̀ kí ó mọ́lẹ̀ sí i yín lára.Kí ó sì ṣàánú fún un yín.
26 Kí Olúwa bojú wò yín;Kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà.” ’
27 “Báyìí ni wọn ó ṣe fi orúkọ mi sára àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, Èmi ó sì bùkún wọn.”