Onídájọ́ 20:28-34 BMY

28 Fínéhásì ọmọ Élíásárì ọmọ Árónì, ní ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ ní iwájú rẹ̀.) Wọ́n béèrè pé, “Ṣe àwa tún le lọ sí ogun pẹ̀lú Bẹ́ńjámínì arákùnrin wa tàbí kí a má lọ?” Olúwa dáhùn pé, “Ẹ lọ nítorí ní ọ̀la ni èmi yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.”

29 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì yàn àwọn ènìyàn tí ó lúgọ (sápamọ́) yí Gíbíà ká.

30 Wọ́n jáde tọ àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì lọ ní ọjọ́ kẹta wọ́n sì dúró ní ipò wọn, wọ́n sì dìde ogun sí Gíbíà bí wọ́n ti ṣe tẹ́lẹ̀ rí.

31 Àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì sì jáde láti pàdé wọn, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì tàn wọ́n jáde kúrò ní ìlú náà. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣẹ́gun àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bí i ti àtijọ́ dé bi pé wọ́n pa bí ọgbọ̀n ọkùnrin ní pápá àti ní àwọn òpópó náà—àwọn ọ̀nà tí ó lọ sí Bẹ́tẹ́lì àti èkejì sí Gíbíà.

32 Nígbà tí àwọn Bẹ́ńjámínì ń wí pé, “Àwa ti ń ṣẹ́gun wọn bí i ti ìṣáájú,” àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá kí a lè fà wọ́n kúrò ní ìlú sí ojú òpópó náà.”

33 Gbogbo àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì dìde kúrò ní ipò wọn, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Báálì Támárì, àwọn ọmọ ogun Ísírẹ́lì tí wọ́n sápamọ́ sínú igbó jáde kúrò níbi tí wọ́n wà ní ìwọ̀ oòrùn Gíbíà.

34 Nígbà náà ni ẹgbàá márùn ún (10,000) àwọn àṣàyàn ológun àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbógun ti Gíbíà láti iwájú ogun náà le gidigidi dé bí i pé àwọn ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì kò funra pé ìparun wà nítòsí.