21 Odò Kísónì agbá wọn lọ,odò àtijọ́ náà, odò Kíṣónì.Má a yan lọ ìwọ ọkàn mi, jẹ́ alágbára pẹ̀lú!
22 Nígbà náà ni pátakò ẹṣẹ̀ ẹsin ki ilẹ̀,nítorí eré sísá, eré sísá àwọn alágbára wọn.
23 ‘Ẹ fi Mérósì,’ bú ni ańgẹ́lì Olúwa wí.‘Ẹ fi àwọn ènìyàn inú rẹ̀ gégùn ún kíkorò,nítorí wọn kò wá sí ìrànlọ́wọ́ OLÚWÁ,láti dojúkọ àwọn alágbára.’
24 “Alábùkún jùlọ nínú àwọn ọmọ obìnrin ni Jáélì,aya Hébérì ará Kénì,alábùkún jùlọ nínú àwọn obìnrin tí ń gbé inú àgọ́.
25 Ó bèèrè omi, ó fún un ní wàrà;ó fi àwo iyebíye tí ó yẹ fún àwọn ọlọ́la fún un ni wàrà dídì.
26 Ó na ọwọ́ rẹ̀ mú ìṣó àgọ́,ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ mú òòlù awọ gbẹ́nàgbẹ́nà.Ó kan Ṣísérà mọ́lẹ̀ pẹ̀lú òòlù ọwọ́ rẹ̀, ó fọ́ ọ ní orí,Ó kàn ẹ̀bátí rẹ̀ mọ́lẹ̀ sinsiǹ.
27 Ní ẹṣẹ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ó ṣubú; ó dúbúlẹ̀.Ní ẹṣẹ̀ rẹ̀, ó wó lulẹ̀;ní ibi tí ó gbé wólẹ̀ sí, níbẹ̀ náà ni ó ṣubú kú.