Onídájọ́ 6:11-17 BMY

11 Ní ọjọ́ kan ańgẹ́lì Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù ófírà èyí ti ṣe ti Jóásìu ará Ábíésérì, níbi tí Gídíónì ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọn ọtí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Mídíánì.

12 Nígbà tí ańgẹ́lì Olúwa fara han Gídíónì, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”

13 Gídíónì dáhùn pé, Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, “Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Éjíbítì wá? Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Mídíánì lọ́wọ́.”

14 Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Ísírẹ́lì sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Mídíánì. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”

15 Gídíónì sì dáhùn pé, “Alàgbà Báwo ni èmi ó ṣe gba Ísírẹ́lì là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Mànásè, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé bàbá mi.”

16 Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Mídíánì láì ku ẹnìkankan.”

17 Gídíónì sì dáhùn pé, nísinsìn yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.