Onídájọ́ 6:33-39 BMY

33 Láìpẹ́ jọjọ àwọn ogun àwọn Mídíánì, ti àwọn Ámálékì àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà oòrùn yóòkù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jọ́dánì wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jésírẹ́lì.

34 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gídíónì, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Ábíésérì láti tẹ̀lé òun.

35 Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Mánásè já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Ásérì, Ṣébúlúnì àti Náfítalì gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.

36 Gídíónì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Ísírẹ́lì là nípaṣẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—

37 kíyèsí, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá ṣẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yóòkù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Ísírẹ́lì là nípaṣẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”

38 Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gídíónì jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì ó sì fún irun àgùntàn náà, páànù omi kan sì kún.

39 Gídíónì sì tún wí fún Olúwa pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan síi. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”