6 Àwọn ará Mídíánì sì pọ́n àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòsì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Mídíánì.
8 Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn. Ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí: mo mú yín gòkè ti Éjíbítì wá, láti oko ẹrú.
9 Mo gbà yín kúrò nínú agbára Éjíbítì àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 Mo wí fún un yín pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín: ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Ámórì, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́ràn sí ohun tí mo sọ.”
11 Ní ọjọ́ kan ańgẹ́lì Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù ófírà èyí ti ṣe ti Jóásìu ará Ábíésérì, níbi tí Gídíónì ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọn ọtí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Mídíánì.
12 Nígbà tí ańgẹ́lì Olúwa fara han Gídíónì, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”