19 Ìtẹ́ náà ní àtẹ̀gùn mẹfa, ère orí ọmọ mààlúù sì wà lẹ́yìn ìtẹ́ náà. Ère kinniun wà ní ẹ̀gbẹ́ kinni keji ibi tí wọn ń gbé apá lé lára ìtẹ́ náà.
20 Ère kinniun mejila wà lórí àwọn àtẹ̀gùn mẹfẹẹfa, meji meji lórí àtẹ̀gùn kọ̀ọ̀kan, ní ẹ̀gbẹ́ kinni keji àtẹ̀gùn náà; kò sí ìjọba orílẹ̀-èdè kankan tí ó tún ní irú ìtẹ́ náà.
21 Wúrà ni wọ́n fi ṣe gbogbo ife ìmumi Solomoni, ati gbogbo àwọn ohun èlò tí ó wà ninu Ilé Igbó Lẹbanoni. Kò sí ẹyọ kan ninu wọn tí wọ́n fi fadaka ṣe, nítorí pé fadaka kò já mọ́ nǹkankan ní àkókò Solomoni.
22 Ó ní ọpọlọpọ ọkọ̀ ojú omi Taṣiṣi tí wọ́n máa ń bá àwọn ọkọ̀ ojú omi Hiramu lọ sí òkè òkun. Ọdún kẹta kẹta ni wọ́n máa ń pada dé, wọn á sì máa kó ọpọlọpọ wúrà, ati fadaka, eyín erin, ìnàkí, ati ẹyẹ ọ̀kín bọ̀.
23 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ọba ṣe lọ́rọ̀, tí ó sì gbọ́n ju gbogbo ọba yòókù lọ.
24 Gbogbo aráyé a sì máa fẹ́ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, láti tẹ́tí sí ọgbọ́n tí Ọlọrun fún un.
25 Ní ọdọọdún ni ọpọlọpọ eniyan máa ń mú ọpọlọpọ ẹ̀bùn àwọn nǹkan tí wọ́n fi fadaka ati wúrà ṣe wá sọ́dọ̀ rẹ̀, pẹlu ẹ̀wù, ati turari olóòórùn dídùn, ẹṣin, ati ìbaaka.