Àwọn Ọba Kinni 10:20-26 BM

20 Ère kinniun mejila wà lórí àwọn àtẹ̀gùn mẹfẹẹfa, meji meji lórí àtẹ̀gùn kọ̀ọ̀kan, ní ẹ̀gbẹ́ kinni keji àtẹ̀gùn náà; kò sí ìjọba orílẹ̀-èdè kankan tí ó tún ní irú ìtẹ́ náà.

21 Wúrà ni wọ́n fi ṣe gbogbo ife ìmumi Solomoni, ati gbogbo àwọn ohun èlò tí ó wà ninu Ilé Igbó Lẹbanoni. Kò sí ẹyọ kan ninu wọn tí wọ́n fi fadaka ṣe, nítorí pé fadaka kò já mọ́ nǹkankan ní àkókò Solomoni.

22 Ó ní ọpọlọpọ ọkọ̀ ojú omi Taṣiṣi tí wọ́n máa ń bá àwọn ọkọ̀ ojú omi Hiramu lọ sí òkè òkun. Ọdún kẹta kẹta ni wọ́n máa ń pada dé, wọn á sì máa kó ọpọlọpọ wúrà, ati fadaka, eyín erin, ìnàkí, ati ẹyẹ ọ̀kín bọ̀.

23 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ọba ṣe lọ́rọ̀, tí ó sì gbọ́n ju gbogbo ọba yòókù lọ.

24 Gbogbo aráyé a sì máa fẹ́ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, láti tẹ́tí sí ọgbọ́n tí Ọlọrun fún un.

25 Ní ọdọọdún ni ọpọlọpọ eniyan máa ń mú ọpọlọpọ ẹ̀bùn àwọn nǹkan tí wọ́n fi fadaka ati wúrà ṣe wá sọ́dọ̀ rẹ̀, pẹlu ẹ̀wù, ati turari olóòórùn dídùn, ẹṣin, ati ìbaaka.

26 Ọpọlọpọ kẹ̀kẹ́ ogun ati ẹlẹ́ṣin ni Solomoni ọba kó jọ, kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ jẹ́ egbeje (1,400), àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbaafa (1,200). Ó fi apá kan ninu wọn sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀ ní Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn yòókù sí ìlú ńláńlá tí ó ń kó àwọn kẹ̀kẹ́ ogun sí káàkiri.