1 Ní ọdún kejidinlogun tí Jeroboamu jọba Israẹli, ni Abijamu gorí oyè ní ilẹ̀ Juda.
2 Ọdún mẹta ló fi jọba ní Jerusalẹmu. Maaka ọmọ Absalomu ni ìyá rẹ̀.
3 Gbogbo irú ẹ̀ṣẹ̀ tí baba Abijamu dá, ni òun náà dá. Kò fi tọkàntọkàn ṣe olóòótọ́ sí OLUWA Ọlọrun rẹ̀ bí Dafidi, baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
4 Sibẹsibẹ, nítorí ti Dafidi, OLUWA Ọlọrun fún Abijamu ní ọmọkunrin kan tí ó gorí oyè lẹ́yìn rẹ̀, ní Jerusalẹmu, tí ó sì dáàbò bo Jerusalẹmu.