Lefitiku 5:11-17 BM

11 “Ṣugbọn bí kò bá ní agbára láti mú àdàbà meji tabi ọmọ ẹyẹlé meji wá, ohun tí yóo mú wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá ni, ìdámẹ́wàá ìwọ̀n efa ìyẹ̀fun tí ó kúnná dáradára, kí ó má fi òróró tabi turari olóòórùn dídùn sórí rẹ̀, nítorí ẹbọ ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ ni.

12 Kí ó gbé ìyẹ̀fun náà tọ alufaa wá, kí alufaa bu ẹ̀kúnwọ́ kan ninu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí, kí ó sì fi rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ sí OLUWA, ẹbọ ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ ni.

13 Bẹ́ẹ̀ ni alufaa yóo ṣe ètùtù fún un nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá, nítorí pé ó ṣe ọ̀kan ninu àwọn ohun tí OLUWA pa láṣẹ pé ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ ṣe, OLUWA yóo sì dáríjì í. Ìyẹ̀fun yòókù yóo di ti alufaa, gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ohun jíjẹ.”

14 OLUWA sọ fún Mose pé:

15 “Bí ẹnikẹ́ni bá ṣèèṣì dẹ́ṣẹ̀ nípa pé kò san àwọn nǹkan tíí ṣe ti OLUWA fún OLUWA, ohun tí yóo mú wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìmúkúrò ẹ̀bi fún OLUWA ni: àgbò kan tí kò ní àbààwọ́n, láti inú agbo aguntan rẹ̀, ìwọ̀n tí wọ́n fi ń wọn fadaka ninu ilé OLUWA ni wọn yóo lò láti fi díyelé àgbò náà; ẹbọ ìmúkúrò ẹ̀bi ni.

16 Yóo san ohun tí ó yẹ kí ó san fún OLUWA tí kò san, pẹlu èlé ìdámárùn-ún rẹ̀ fún alufaa, alufaa yóo sì fi àgbò ẹbọ ẹ̀bi náà ṣe ètùtù fún un, a óo sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì í.

17 “Bí ẹnikẹ́ni bá dẹ́ṣẹ̀, tí ó ṣe ọ̀kan ninu àwọn nǹkan tí OLUWA pa láṣẹ pé ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ ṣe, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò mọ̀, sibẹ ó jẹ̀bi, yóo sì san ìtanràn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.