12 láti inú ẹ̀yà Dani, ó rán Amieli, ọmọ Gemali;
13 láti inú ẹ̀yà Aṣeri, ó rán Seturu, ọmọ Mikaeli;
14 láti inú ẹ̀yà Nafutali, ó rán Nahibi ọmọ Fofisi;
15 láti inú ẹ̀yà Gadi, ó rán Geueli ọmọ Maki.
16 Orúkọ àwọn ọkunrin tí Mose rán láti lọ ṣe amí ilẹ̀ náà nìyí. Mose sì yí orúkọ Hoṣea ọmọ Nuni pada sí Joṣua.
17 Mose rán wọn láti lọ ṣe amí ilẹ̀ náà. Kí wọ́n tó lọ, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà ìhà àríwá, kí ẹ tọ̀ ọ́ lọ sí ìhà gúsù ilẹ̀ Kenaani, kí ẹ wá lọ sí àwọn orí òkè.
18 Ẹ wo irú ilẹ̀ tí ilẹ̀ Kenaani jẹ́, àwọn eniyan mélòó ló ń gbé ibẹ̀ ati pé báwo ni wọ́n ṣe lágbára sí.